Tuesday 15 June 2021

Ọ̀YẸ̀KÚ MÉJÌ

ODU IFA OYEKU MEJI

Èkìtì bámúbá ní í pẹ̀kun ìpópó 

A dífá fún Ikúyẹ̀ 

Èyì tí í ṣe ọmọ bíbí inú Àgbọnmìrègún 

Lọ́jọ́ tí ikú ń filé rẹ̀ ńkàn firii 

Tí àrùn ń filé rẹ̀ ńkàn firii.....

Wọ́n ní kó kárale kó rúbọ:

Obì meji, òròmọdìyẹ, òbúkọ, ẹ̀kọ, àkàrà, 

Àti aṣọ pupa 

Ikúyẹ̀ kábọmọ́ra ó rúbọ 

Wọ́n ṣe síse Ifá fún un.

Bí ikú ṣe yẹ̀ lórí rẹ̀ nìyẹn 

Ó wá ń jó, ó ń yọ̀

Ó ń yin àwọn awo 

Awo ń yin Ifá, 

Ifá ń yin Olódùmarè 

Ó ní ǹjẹ́ rírú ẹbọ a máa gbeni 

Èrù àrùkèṣù a má a dá ládàjúú 

Kò pẹ́ kò jìnà 

Ifá wá bá mi láìkú kàngiri 

Àìkú kàngiri ni à ń bá awo lẹ́sẹ̀ Ọbarìṣà.

Ikúyẹ̀ wá fi ìyẹ̀rẹ̀ ohùn bọnu wípé: 

Ǹjẹ́ ikú mà yẹ̀ lóríì mi ò 

Òkùtù àyẹ̀rẹ̀ ikú yẹ̀,

Àrùn mà yẹ̀ lórí ì mi ò 

Òkùtù àyẹ̀rẹ̀ àrún yẹ̀

Gbogbo ajogun ibi mà yẹ̀ lóríì mi ò 

Òkùtù àyẹ̀rẹ̀ ikú yẹ̀.

Ikú òjijì yíò yẹ̀ lóríi gbogbo wa o

Àààṣẹẹẹ!

This Ifa verse was chanted by Oba Edu Faniyi Osagbami, professor of Ifa studies, University of Ifa.

Please add your own chant from Ọ̀yẹ̀kú Méjì to it.

Copyright: © 2021

No comments:

Post a Comment

Related Posts Plugin for WordPress, Blogger...